Categories
ÌWÉ ÒWE

ÌWÉ ÒWE 20

1 Ẹlẹ́yà ni ọtí waini,

aláriwo ní ọtí líle,

ẹnikẹ́ni tí a bá fi tànjẹ kò gbọ́n.

2 Ibinu ọba dàbí bíbú kinniun,

ẹni tí ó bá mú ọba bínú fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu.

3 Nǹkan iyì ni pé kí eniyan máa yẹra fún ìjà,

ṣugbọn òmùgọ̀ eniyan níí máa ń jà.

4 Ọ̀lẹ kì í dáko ní àkókò,

nítorí náà, nígbà ìkórè, kò ní rí nǹkankan kó jọ.

5 Èrò ọkàn eniyan dàbí omi jíjìn,

ẹni tí ó bá ní ìmọ̀ ló lè fà á jáde.

6 Ọ̀pọ̀ eniyan a máa ka ara wọn kún olóòótọ́,

ṣugbọn níbo la ti lè rí ẹyọ ẹnìkan tó jẹ́ olódodo?

7 Olódodo a máa rìn ní ọ̀nà òtítọ́,

ibukun ni fún àwọn ọmọ rẹ̀ tí wọ́n tẹ̀lé e.

8 Nígbà tí ọba bá jókòó sórí ìtẹ́ ìdájọ́ rẹ̀,

ojú ni yóo fi gbọn àwọn ẹni ibi dànù.

9 Ta ló lè sọ pé ọkàn òun mọ́,

ati pé òun mọ́, òun kò ní ẹ̀ṣẹ̀?

10 Ayédèrú òṣùnwọ̀n jẹ́ ohun ìríra lójú OLUWA.

11 Ọmọde pàápàá a máa fi irú eniyan tí òun jẹ́ hàn nípa ìṣe rẹ̀,

bí ohun tí ó ṣe dára, tí ó sì tọ̀nà.

12 Ati etí tí ń gbọ́ràn, ati ojú tí ń ríran,

OLUWA ló dá ekinni-keji wọn.

13 Má fẹ́ràn oorun àsùnjù, kí o má baà di talaka,

lajú, o óo sì ní oúnjẹ ní àníṣẹ́kù.

14 “Èyí kò dára, kò dára” ni ẹni tí ń rajà máa ń wí,

bí ó bá lọ tán, a máa fọ́nnu ọjà ọ̀pọ̀ tí ó rà.

15 Wúrà ń bẹ, òkúta olówó iyebíye sì wà lọpọlọpọ,

ṣugbọn ọ̀rọ̀ ìmọ̀ ni ohun ọ̀ṣọ́ olówó iyebíye.

16 Gba ẹ̀wù ẹni tí ó bá ṣe onídùúró fún àlejò,

gba aṣọ ẹni tí ó ṣe onígbọ̀wọ́ ẹni tí kò mọ̀ rí.

17 Oúnjẹ tí a bá rí lọ́nà èrú máa ń dùn lẹ́nu eniyan,

ṣugbọn nígbà tí a bá jẹ ẹ́ tán, ẹnu ẹni a máa kan.

18 Ìmọ̀ràn níí fìdí ètò múlẹ̀,

gba ìtọ́sọ́nà kí o tó lọ jagun.

19 Ẹni tí ó ń ṣe òfófó káàkiri a máa tú ọpọlọpọ àṣírí,

nítorí náà má ṣe bá ẹlẹ́jọ́ kẹ́gbẹ́.

20 Bí eniyan bá ń fi baba tabi ìyá rẹ̀ bú,

àtùpà rẹ̀ yóo kú láàrin òkùnkùn biribiri.

21 Ogún tí a fi ìkánjú kójọ níbẹ̀rẹ̀,

kì í ní ibukun nígbẹ̀yìn.

22 Má sọ pé o fẹ́ fi burúkú san burúkú,

gbẹ́kẹ̀lé OLUWA, yóo sì gbà ọ́.

23 Ayédèrú òṣùnwọ̀n jẹ́ ohun ìríra lójú OLUWA,

ìwọ̀n èké kò dára.

24 OLUWA ní ń tọ́ ìṣísẹ̀ ẹni,

eniyan kò lè ní òye ọ̀nà ara rẹ̀.

25 Ronú jinlẹ̀ kí o tó jẹ́jẹ̀ẹ́ fún OLUWA,

kí o má baà kábàámọ̀ rẹ̀.

26 Ọba tó gbọ́n a máa fẹ́ eniyan burúkú dànù,

a sì lọ̀ wọ́n mọ́lẹ̀.

27 Ẹ̀mí eniyan ni fìtílà OLUWA,

tíí máa wá gbogbo kọ́lọ́fín inú rẹ̀ kiri.

28 Ìfẹ́ ati òtítọ́ níí mú kí ọba pẹ́,

òdodo níí sì ń gbé ìjọba rẹ̀ ró.

29 Agbára ni ògo ọ̀dọ́,

ewú sì ni ẹwà àgbà.

30 Ìjìyà tó fa ọgbẹ́ a máa mú ibi kúrò,

pàṣán a máa mú kí inú mọ́.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *