Categories
ISIKIẸLI

ISIKIẸLI 19

Orin Arò

1 OLUWA ní kí n sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn nítorí àwọn olórí Israẹli,

2 kí n sọ pé:

Abo kinniun pataki ni ìyá rẹ láàrin àwọn kinniun!

Ó dùbúlẹ̀ láàrin àwọn ọ̀dọ́ kinniun,

ó ń tọ́jú àwọn ọmọ rẹ̀.

3 Ó tọ́ ọ̀kan ninu àwọn ọmọ rẹ̀ dàgbà;

ó di ọ̀dọ́ kinniun.

Ó kọ́ ọ bí wọ́n tí ń ṣe ọdẹ,

ó sì ń pa eniyan jẹ.

4 Àwọn eniyan ayé gbọ́ nípa rẹ̀,

wọ́n tàn án sinu kòtò wọn.

Wọ́n fi ìwọ̀ kọ́ ọ nímú,

wọ́n sì fà á lọ sí ilẹ̀ Ijipti.

5 Nígbà tí abo kinniun náà rí i pé ọwọ́ tẹ ọmọ òun,

ati pé igbẹkẹle òun ti dòfo,

ó mú òmíràn ninu àwọn ọmọ rẹ̀,

ó tọ́ ọ di ọ̀dọ́ kinniun.

6 Ó ń yan kiri láàrin àwọn kinniun;

nítorí ó ti di ọ̀dọ́ kinniun tí ó lágbára,

ó kọ́ bí wọn tí ń ṣe ọdẹ,

ó sì ń pa eniyan jẹ.

7 Ó wó ilé ìṣọ́ wọn lulẹ̀;

ó sọ ìlú wọn di ahoro.

Ẹ̀rù ba gbogbo Ilẹ̀ náà, ati gbogbo àwọn tí ń gbé ibẹ̀,

nígbà tí wọ́n gbọ́ bíbú rẹ̀.

8 Àwọn orílẹ̀-èdè bá dójú lé e,

wọ́n dẹ tàkúté fún un ní gbogbo ọ̀nà,

wọ́n da àwọ̀n wọn bò ó,

wọ́n sì mú un ninu kòtò tí wọn gbẹ́ fún un.

9 Wọ́n sọ ìwọ̀ sí i nímú,

wọ́n gbé e jù sinu àhámọ́,

wọ́n sì fà á lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Babiloni.

Wọ́n fi sí àtìmọ́lé,

kí wọ́n má baà gbọ́ ohùn rẹ̀ mọ́ lórí àwọn òkè Israẹli.

10 Ìyá rẹ dàbí àjàrà inú ọgbà

tí a gbìn sí ẹ̀gbẹ́ odò;

ó rúwé, ó yọ ẹ̀ka,

nítorí ó rí omi lọpọlọpọ.

11 Ẹ̀ka rẹ̀ tí ó lágbára

ni a fi gbẹ́ ọ̀pá àṣẹ fún àwọn olórí.

Ó dàgbà, ó ga fíofío, láàrin àwọn igi igbó.

Ó rí i bí ó ti ga, tí ẹ̀ka rẹ̀ sì pọ̀.

12 Ṣugbọn a fa àjàrà náà tu pẹlu ibinu,

a sì jù ú sílẹ̀.

Afẹ́fẹ́ ìlà oòrùn mú kí ó gbẹ,

gbogbo èso rẹ̀ sì rẹ̀ dànù.

Igi rẹ̀ tí ó lágbára gbẹ, iná sì jó o.

13 Nisinsinyii, a ti tún un gbìn sinu aṣálẹ̀,

ninu ilẹ̀ gbígbẹ níbi tí kò sí omi.

14 Iná ṣẹ́ lára igi rẹ̀,

ó sì jó gbogbo ẹ̀ka ati èso rẹ̀.

Kò sì ní igi tí ó lágbára mọ́,

tí a lè fi gbẹ́ ọ̀pá àṣẹ fún ọba.

Dájúdájú ọ̀rọ̀ arò ni ọ̀rọ̀ yìí, ó sì ti di orin arò.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *