Categories
AISAYA

AISAYA 9

Ọba Lọ́la

1 Ṣugbọn kò ní sí ìṣúdudu fún ẹni tí ó wà ninu ìnira. Ní ìgbà àtijọ́, ó sọ ilẹ̀ Sebuluni ati ilẹ̀ Nafutali di yẹpẹrẹ, ṣugbọn nígbà ìkẹyìn yóo ṣe ilẹ̀ àwọn tí ó ń gbé apá ọ̀nà òkun lógo, títí lọ dé òdìkejì odò Jọdani, ati Galili níbi tí àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè mìíràn ń gbé.

2 Àwọn tí ń rìn ninu òkùnkùn ti rí ìmọ́lẹ̀ ńlá.

Ìmọ́lẹ̀ sì ti tàn sí àwọn tí ń gbé ninu òkùnkùn biribiri.

3 Ó ti bukun orílẹ̀-èdè náà.

Ó ti fi kún ayọ̀ wọn;

wọ́n ń yọ̀ níwájú rẹ̀, bí ayọ̀ ìgbà ìkórè.

Bí inú àwọn eniyan ti máa ń dùn nígbà tí wọ́n bá ń pín ìkógun.

4 Nítorí pé ó ti ṣẹ́ àjàgà tí ó wọ̀ wọ́n lọ́rùn,

ati ọ̀pá tí wọn fí ń ru ẹrù sí èjìká,

ati kùmọ̀ àwọn tí ń fìyà jẹ wọ́n.

Ó ti ṣẹ́ wọn, bí ìgbà tí ó ṣẹ́ ti àwọn ará Midiani.

5 Gbogbo bàtà àwọn ológun, tí ń kilẹ̀ lójú ogun,

ati gbogbo ẹ̀wù tí wọ́n ti yí mọ́lẹ̀ ninu ẹ̀jẹ̀ ni a óo dáná sun,

iná yóo sì jó wọn run.

6 Nítorí a bí ọmọ kan fún wa,

a fún wa ní ọmọkunrin kan.

Òun ni yóo jọba lórí wa.

A óo máa pè é ní Ìyanu, Olùdámọ̀ràn,

Ọlọrun alágbára, Baba ayérayé,

Ọmọ-Aládé alaafia.

7 Ìjọba rẹ̀ yóo máa tóbi sí i,

alaafia kò sì ní lópin ní ìjọba rẹ̀ lórí ìtẹ́ Dafidi.

Yóo fìdí rẹ̀ múlẹ̀,

yóo sì gbé e ró pẹlu ẹ̀tọ́ ati òdodo,

láti ìgbà yìí lọ, títí ayérayé.

Ìtara OLUWA àwọn ọmọ ogun ni yóo ṣe èyí

OLUWA yóo Jẹ Israẹli Níyà

8 OLUWA ranṣẹ ìdájọ́ sí Jakọbu,

àní, sórí àwọn ọmọ Israẹli.

9 Gbogbo eniyan ni yóo mọ̀,

àwọn ará Efuraimu ati àwọn ará Samaria,

àwọn tí wọn ń fọ́nnu pẹlu ìgbéraga pé:

10 Ṣé bíríkì ni wọ́n fi kọ́ àwọn ilé tí ó wó lulẹ̀?

Òkúta gbígbẹ́ ni a óo fi tún wọn kọ́.

Igi sikamore ni a fi kọ́ èyí tí wọ́n dà wó,

ṣugbọn igi kedari dáradára ni a óo lò dípò wọn.

11 Nítorí náà OLUWA ti gbé ọ̀tá dìde sí wọn:

Ó ti rú àwọn ọ̀tá wọn sókè sí wọn:

12 Àwọn ará Siria láti ìhà ìlà oòrùn,

ati àwọn ará Filistia láti ìhà ìwọ̀ oòrùn;

wọn óo gbé Israẹli mì.

Sibẹsibẹ inú OLUWA kò rọ̀,

bẹ́ẹ̀ ni kò dá ọwọ́ ìjà rẹ̀ dúró.

13 Sibẹsibẹ àwọn ọmọ Israẹli kò pada sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó jẹ wọ́n níyà,

bẹ́ẹ̀ ni wọn kò wá OLUWA àwọn ọmọ-ogun.

14 Nítorí náà, OLUWA yóo fi ìyà jẹ Israẹli.

Ní ọjọ́ kan ṣoṣo, yóo gé Israẹli lórí ati nírù.

15 Àwọn àgbààgbà ati àwọn ọlọ́lá wọn ni orí,

àwọn wolii tí ń kọ́ àwọn eniyan ní ẹ̀kọ́ èké sì ni ìrù

16 Àwọn tí ń darí àwọn eniyan wọnyi ń ṣì wọ́n lọ́nà ni,

àwọn tí wọn ń tọ́ sọ́nà sì ń já sinu ìparun.

17 Nítorí náà, OLUWA kò láyọ̀ lórí àwọn ọdọmọkunrin wọn,

àánú àwọn aláìníbaba ati àwọn opó wọn kò sì ṣe é

nítorí pé aṣebi ni gbogbo wọn, wọn kò sì mọ Ọlọrun,

ọ̀rọ̀ burúkú ni wọ́n sì ń fi ẹnu wọn sọ.

Sibẹsibẹ inú OLUWA kò rọ̀,

bẹ́ẹ̀ ni kò dá ọwọ́ ìjà rẹ̀ dúró.

18 Ìwà burúkú wọn ń jó bí iná,

tí ń jó ẹ̀gún wẹ́wẹ́ ati ẹ̀gún ọ̀gàn.

Ó ń jó bíi igbó ńlá, ó sì ń yọ èéfín sókè lálá.

19 Nítorí ibinu OLUWA àwọn ọmọ ogun, ilẹ̀ náà jóná,

àwọn eniyan ibẹ̀ dàbí èpò tí a dà sinu iná

ẹnikẹ́ni kò sì dá ẹnìkejì rẹ̀ sí.

20 Wọ́n ń já nǹkan gbà lọ́tùn-ún, wọ́n ń jẹ ẹ́,

sibẹ ebi ń pa wọ́n.

Wọ́n ń jẹ àjẹrun lósì,

sibẹ wọn kò yó,

àwọn eniyan sì ń pa ara wọn jẹ.

21 Àwọn ará Manase ń bá àwọn ará Efuraimu jà,

bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Efuraimu náà ń bá àwọn ará Manase jà.

Àwọn mejeeji wá dojú ìjà kọ Juda.

Sibẹsibẹ inú OLUWA kò rọ̀,

bẹ́ẹ̀ ni kò dáwọ́ ìjà rẹ̀ dúró.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *