Categories
AISAYA

AISAYA 56

Gbogbo Orílẹ̀-Èdè ni yóo Wà lára Àwọn Eniyan Ọlọrun

1 OLUWA ní: “Ẹ máa dá ẹjọ́ ẹ̀tọ́,

kí ẹ sì máa ṣe òdodo;

nítorí ìgbàlà mi yóo dé láìpẹ́,

ẹ óo sì rí ìdáǹdè mi.

2 Ayọ̀ ń bẹ fún gbogbo ẹni tí ó bá ń ṣe bẹ́ẹ̀,

ati fún ẹni tí ó bá ń tẹ̀lé e,

tí ó ń ṣọ́ra, tí kò rú òfin ọjọ́ ìsinmi,

tí kò sì fi ọwọ́ rẹ̀ ṣe nǹkan burúkú.”

3 Kí àjèjì tí ó faramọ́ OLUWA má sọ pé,

“Dájúdájú OLUWA yóo yà mí kúrò láàrin àwọn eniyan rẹ̀.”

Kí ìwẹ̀fà má sì sọ pé,

“Wò ó! Mo dàbí igi gbígbẹ.”

4 Nítorí OLUWA ní,

“Bí ìwẹ̀fà kan bá pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́,

tí ó bá ṣe ohun tí mo fẹ́,

tí ó sì di majẹmu mi mú gbọningbọnin,

5 n óo fún wọn ní ipò láàrin àgbàlá mi,

ati ìrántí tí ó dára, ju ọmọkunrin ati ọmọbinrin lọ.

Orúkọ tí kò ní parẹ́ laelae, ni n óo fún wọn.

6 “Àwọn àjèjì tí ó bá darapọ̀ mọ́ OLUWA, tí wọn ń sìn ín,

tí wọn fẹ́ràn rẹ̀, tí wọn sì ń ṣe iranṣẹ rẹ̀,

gbogbo àwọn tí ó bá pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, tí kò sọ ọ́ di ohun ìríra,

tí ó sì di majẹmu mi mú gbọningbọnin,

7 n óo mú wọn wá sí orí òkè mímọ́ mi,

n óo jẹ́ kí inú wọn máa dùn ninu ilé adura mi.

Ọrẹ sísun ati ẹbọ wọn, yóo jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà lórí pẹpẹ mi;

nítorí ilé adura fún gbogbo eniyan, ni a óo máa pe ilé mi.”

8 OLUWA Ọlọrun tí ń kó àwọn tí ogun túká ní Israẹli jọ sọ pé,

“N óo tún kó àwọn mìíràn jọ,

kún àwọn tí mo ti kọ́ kó jọ.”

A ti Dá Àwọn Olórí Israẹli lẹ́bi

9 Gbogbo ẹ̀yin orílẹ̀-èdè láti òkèèrè, ẹ máa bọ̀,

gbogbo yín ẹ máa bọ̀ bí ẹranko inú ìgbẹ́, ẹ wá jẹ àjẹrun.

10 Afọ́jú ni àwọn aṣọ́de Israẹli

gbogbo wọn kò mọ nǹkankan.

Ajá tí ó yadi ni wọ́n,

wọn kò lè gbó;

oorun ni wọ́n fẹ́ràn.

Wọn á dùbúlẹ̀, wọn á máa lá àlá.

11 Wọ̀bìà ni wọ́n, alájẹkì,

wọn kì í yó.

Àwọn olùdarí wọn pàápàá kò mọ nǹkankan.

Gbogbo wọn ti tẹ̀ sí ọ̀nà ara wọn,

olukuluku wọn ń wá èrè fún ara rẹ̀.

12 Wọn á máa sọ pé: “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á mu waini,

ẹ jẹ́ kí á mu ọtí líle ní àmuyó,

bí òní ṣe rí ni ọ̀la yóo rí, yóo dùn tayọ.”

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *