Categories
AISAYA

AISAYA 50

1 OLUWA ní:

OLUWA ní:

“Ìwé ìkọ̀sílẹ̀ tí mo fi kọ àwọn eniyan mi sílẹ̀ dà?

Ta ni mo tà yín fún,

tí mo jẹ lówó?

Ẹ wò ó! Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ yín ni a ṣe tà yín,

nítorí àìdára yín ni mo ṣe kọ̀ yín sílẹ̀.

2 “Kí ló dé tí mo wá àwọn eniyan mi tí n kò rí ẹnìkan;

mo pè, ẹnikẹ́ni kò dá mi lóhùn?

Ṣé n kò lágbára tó láti rà wọ́n pada ni;

àbí n kò lágbára láti gba ni là?

Wò ó! Ìbáwí lásán ni mo fi gbẹ́ omi òkun,

tí mo sì fi sọ odò tí ń ṣàn di aṣálẹ̀,

omi wọn gbẹ,

òùngbẹ gbẹ àwọn ẹja inú wọn pa,

wọ́n kú, wọ́n sì ń rùn.

3 Mo da òkùnkùn bo ojú ọ̀run bí aṣọ,

mo ṣe aṣọ ọ̀fọ̀ ní ìbora fún wọn.”

Ìgbọràn Iranṣẹ OLUWA

4 OLUWA Ọlọrun ti fi ọ̀rọ̀ ìmọ̀ sí mi lẹ́nu.

Kí n lè mọ bí a tií gba àwọn tí ọkàn wọn rẹ̀wẹ̀sì níyànjú.

Ojoojumọ ni ó ń ṣí mi létí láràárọ̀,

kí n lè máa gbọ́rọ̀ bí àwọn akẹ́kọ̀ọ́.

5 OLUWA Ọlọrun ti ṣí mi létí,

n kò sì ṣe oríkunkun,

tabi kí n pada sẹ́yìn.

6 Mo tẹ́ ẹ̀yìn sílẹ̀ fún àwọn tí ń nani lẹ́gba;

mo sì kọ ẹ̀rẹ̀kẹ́ sí àwọn tí ń fa eniyan ní irùngbọ̀n tu.

N kò fojú pamọ́ nítorí ẹ̀gàn,

bẹ́ẹ̀ ni n kò gbójú sá fún itọ́ títu síni lójú.

7 OLUWA Ọlọrun ń ràn mí lọ́wọ́,

nítorí náà ojú kò tì mí;

nítorí náà mo múra gírí,

mo jẹ́ kí ojú mi le koko,

mo sì mọ̀ pé ojú kò ní tì mí.

8 Ẹni tí yóo dá mi láre wà nítòsí,

ta ló fẹ́ bá mi jà?

Ta ló fẹ́ fi ẹ̀sùn kàn mí?

Kí olúwarẹ̀ súnmọ́ tòsí mi,

kí á jọ kojú ara wa?

9 Wò ó! OLUWA Ọlọrun ń ràn mí lọ́wọ́,

ta ni yóo dá mi lẹ́bi?

Gbogbo wọn ni yóo gbọ̀n dànù bí aṣọ,

kòkòrò yóo sì jẹ wọ́n.

10 Ta ló bẹ̀rù OLUWA ninu yín,

tí ń gbọ́ràn sí iranṣẹ rẹ̀ lẹ́nu,

tí ń rìn ninu òkùnkùn,

tí kò ní ìmọ́lẹ̀,

ṣugbọn sibẹ, tí ó gbẹ́kẹ̀lé OLUWA,

tí ó fẹ̀yìn ti Ọlọrun rẹ̀.

11 Gbogbo ẹ̀yin tí ẹ̀ ń dáná,

tí ẹ tan iná yí ara yín ká,

ẹ máa rìn lọ ninu iná tí ẹ dá;

ẹ máa la iná tí ẹ fi yí ara yín ká kọjá.

Bẹ́ẹ̀ ni n óo ṣe fun yín.

Ẹ óo wà ninu ìrora.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *